Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sefanáyà 3:7-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Èmi wí fún ìlú náà wí pé‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi,ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúròbí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n níyà tó.Ṣùgbọ́n ṣíbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtaraláti ba iṣẹ́ wọn jẹ́.

8. Nítorí náà ẹ dúró dèmi,” ni Olúwa wí,“títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò dìde si ohun ọdẹ; nítoríìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ kíèmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ àti láti rú ìbínú jádesórí wọn, àní gbogbo ibínú gbígbóná mi.Nítorí, a ó fi iná owú ibínú jẹ gbogbo ayé run.

9. “Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́,nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa,láti fi ọkàn kan sìnín.

10. Láti òkè odò Etiópíà,àwọn olùsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká,yóò mú ọrẹ wá fún mi.

11. Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútìnítorí gbogbo ìsẹ́ni tí ó ti ṣesí mi, nígbà náà ni èmi yóò mukúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn.Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́ní òkè mímọ́ mi.

Ka pipe ipin Sefanáyà 3