Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sefanáyà 2:8-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. “Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Móábù,àti ẹlẹ́yà àwọn Ámónì,àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi,tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.

9. Nítorí náà, bí Èmi tí wà,”ni Olúwa Sódómù wí, Ọlọ́run àwọn Ísírẹ́lì,“Ní tòótọ́ Móábù yóò dàbí Sódómùàti Ámónì yóò sì dàbí Gòmórà,ibi tí ó kún fún yèrèpèàti ihó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé.Ìyòókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn;àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi niyóò jogún ilẹ̀ wọn.”

10. Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn,nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa alágbára ṣe ẹlẹ́yà.

Ka pipe ipin Sefanáyà 2