3. Báwo ní yóò ti pẹ́ tó, Olúwatí àwọn ẹni búburúyóò kọ orin ayọ̀?
4. Wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìgbérága jáde;gbogbo àwọn olùṣebúburúkún fún ìṣògo.
5. Wọ́n fọ́ àwọn ènìyàn Rẹ túútúú, Olúwa:wọ́n pọ́n ilẹ̀ ìní Rẹ̀ lójú.
6. Wọ́n pa àwọn opó àti àlejò,wọ́n sì pa àwọn ọmọ aláìní baba,
7. Wọ́n sọ pé, “Olúwa kò rí i;Ọlọ́run Jákọ́bù kò sì kíyèsí i.”
8. Kíyèsí i, ẹ̀yin aláìlóye nínú àwọn ènìyànẹ̀yin aṣiwèrè, nígbà wo ni ẹ̀yin yóò lóye?
9. Ẹni tí ó gbin etí, ó lè ṣe aláìgbọ́ bi?Ẹni tí ó dá ojú?Ó ha lè ṣe láìríran bi?
10. Ẹni tí ń bá orílẹ̀ èdè wí, ṣé kò lè tọ́ ni sọ́nà bí?Ẹni ti ń kọ́ ènìyàn ha lè ṣàìní ìmọ̀ bí?
11. Olúwa mọ èrò inú ènìyàn;ó mọ̀ pé aṣán ni wọ́n.
12. Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tíìwọ báwí, Olúwa,ẹni tí ìwọ kọ́ nínú òfin Rẹ;
13. Ìwọ gbà á kúrò nínú ọjọ́ ibi,títí a ó fi wa ihò sílẹ̀ fún ẹni búburú.
14. Nítorí Olúwa kò ní kọ̀ àwọn ènìyàn Rẹ̀ sílẹ̀;Òun kò sì ní kọ ilẹ̀ ìní Rẹ̀ sílẹ̀.
15. Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo,àti gbogbo àwọn ọlọ́kàndídúró ṣinṣin yóò tẹ̀ lé e lẹ́yìn.