Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 94:18-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Nígbà tí mo sọ pé “ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”, Olúwa, ìfẹ́ Rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.

19. Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi,ìtùnú Rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.

20. Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú Rẹẹni tí ń fí òfin dìmọ̀ ìwà ìkà?

21. Wọ́n kó ara wọn jọ si olódodowọ́n sì ń dá àwọn aláìsẹ̀ lẹ́bi sí ikú.

22. Ṣùgbọ́n, Olúwa ti di odi alágbára mi,àti Ọlọ́run mi ni àpáta nínú ẹnití mo ti ń gba ààbò.

23. Òun yóò san ẹ̀san ibi wọn fún wọnyóò sì pa wọ́n run nítorí búburú wọn Olúwa Ọlọ́run wa yóò pa wọ́n run.

Ka pipe ipin Sáàmù 94