Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 94:15-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo,àti gbogbo àwọn ọlọ́kàndídúró ṣinṣin yóò tẹ̀ lé e lẹ́yìn.

16. Ta ni yóò dìde fún misí àwọn olùṣe búburú?Tàbí ta ni yóò dìde sí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ fún mi?

17. Bí kò ṣe pé Olúwa fún mi ní ìrànlọ́wọ́,èmi fẹ́rẹ̀ má a gbé ní ilẹ̀ tí ó dákẹ́

18. Nígbà tí mo sọ pé “ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”, Olúwa, ìfẹ́ Rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.

19. Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi,ìtùnú Rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.

20. Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú Rẹẹni tí ń fí òfin dìmọ̀ ìwà ìkà?

21. Wọ́n kó ara wọn jọ si olódodowọ́n sì ń dá àwọn aláìsẹ̀ lẹ́bi sí ikú.

22. Ṣùgbọ́n, Olúwa ti di odi alágbára mi,àti Ọlọ́run mi ni àpáta nínú ẹnití mo ti ń gba ààbò.

Ka pipe ipin Sáàmù 94