Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 82:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọlọ́run ń ṣàkóso nínú ìpéjọpọ̀ ńlá,ó ṣe ìdájọ́ láàárin àwọn “ọlọ́run òrìṣà”:

2. “Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa gbèjà àwọn aláìsòdodokí ó sì ṣe ojú ìṣájú sí àwọn ènìyàn búburú?

3. Gbèjà àwọn aláìlágbára àti aláìní baba;ṣe ìtọ́jú ẹ̀tọ́ àwọn aláìní àti ẹni ìnilára.

4. Gba àwọn aláìlágbára àti aláìní;gbà wọ́n kùró lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú.

5. “Wọn kò mọ̀ ohunkankan,wọn kò lóye ohunkankan.Wọn ń rìn kiri nínú òkùnkùn;a ni gbogbo ìpínlẹ̀ ayé.

6. “Mo wí pé, ‘Ẹyin ní “Ọlọ́run òrìṣà”;ẹ̀yin ní gbogbo ọmọ ọ̀gá ògo jùlọ.’

7. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin o kú bí ènìyàn lásán;ẹ̀yin ó ṣubú bí ọ̀kan nínú ọmọ aládé.”

8. Dìde Ọlọ́run ṣe ìdájọ́ ayé,nítorí gbogbo orílẹ̀ èdè ni ìní Rẹ.

Ka pipe ipin Sáàmù 82