Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 39:6-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Nítòótọ́ ni olúkúlùkù ń rìn kiri bí òjìji.Nítòótọ́ ni wọ́n ń yọ ara wọn lẹ́nu lórí asán;wọ́n ń kó ọrọ̀ jọ,wọn kò sì mọ ẹni tí yóò ko lọ.

7. Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí, Olúwa,kín ni mo ń dúró dè?Ìrètí mí ń bẹ ní ọ̀dọ̀ Rẹ.

8. Gbà mí lọ́wọ́ ìrékọjá mi gbogbo.Kí o má sì sọ mí di ẹni ẹ̀gànàwọn ènìyàn búburú.

9. Mo dákẹ́ jẹ́ẹ́;èmi kò sì ya ẹnu mi,nítorí wí pé ìwọ ni ó ṣe é.

10. Mú ìnà Rẹ̀ kúrò ní ara mi;èmí ṣègbé tán nípa ìlù ọwọ́ Rẹ.

11. Ìwọ fi ìbáwí kìlọ̀fún ènìyàn nítorí ẹ̀ṣẹ̀,ìwọ a mú ẹwà Rẹ parunbí kòkòrò aṣọ;nítòótọ́ asán ni ènìyàn gbogbo.

12. “Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa,kí o sì fetí sí igbe mi;kí o má ṣe di etí Rẹ sí ẹkún minítorí àlejò ni èmi lọ́dọ̀ Rẹàti àtìpó, bí gbogbo àwọn baba mi ti rí.

13. Dá mi sí, kí èmi lè ní agbára,kí èmi tó lọ kúrò níhín-ín yìí,àti kí èmi ó tó ṣe aláìsí.”

Ka pipe ipin Sáàmù 39