Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 37:33-39 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́kì yóò sì dá a lẹ́bi,nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ Rẹ̀.

34. Dúró de Olúwa,kí o sì má a pa ọ̀nà Rẹ̀ mọ́,yóò sì gbé ọ lékèláti jogún ilẹ̀ náà:Nígbà tí a bágé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.

35. Èmí ti rí ènìyàn búburútí n hu ìwà ìkà,ó sì fi ara Rẹ̀ gbilẹ̀ bíigi tútù ńlá.

36. Ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan síi ó kọjá lọ,sì kíyèsí, kò sì sí mọ́;bi ó tílẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri,ṣùgbọ́n a kò le è ri.

37. Má a kíyèsí ẹni pípé,kí o sì wo adúró ṣinṣin,nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.

38. Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjání a ó parun papọ̀;ìran àwọn ènìyàn búburúní a ó gé kúrò.

39. Ìgbàlà àwọn adúró ṣinṣinwa láti ọ̀dọ̀ Olúwa:òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú

Ka pipe ipin Sáàmù 37