7. Nítorí pé, ní àìnídìí ní wọ́n dẹàwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi,ní àìnídìí ni wọ́n wa kòtòfún ọkàn mi.
8. Jẹ́ kí ìparun kí ó wá síorí wọn lójijì.Àwọ̀n Rẹ̀ tí ó dẹ pamọ́,kí ó mú àwọn tìkálára wọn;kí wọn ṣubú sínú kòtòsí ìparun ara Rẹ̀.
9. Nígbà náà ni ọkàn miyóò yọ̀ nínú Olúwa,àní ayọ̀ ńlá nínú ìgbàlà Rẹ̀.
10. Gbogbo egúngún mi yóò wí pé,“ìwọ Olúwa,ta ni ó dà bí i Rẹ̀?O gba talákà làlọ́wọ́ àwọn tí ó lágbárajù wọ́n lọ,talákà àti aláìnílọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”
11. Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde;wọ́n bi mi léèrè àwọn ohuntí èmi kò mọ̀.
12. Wọ́n fi búburú san ire fún mi;láti sọ ọkàn mi di òfo.
13. Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni,nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn,mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀;mo fi ààwẹ̀ pọ́n ara mi lójú.Mo gba àdúrà pẹ̀lú ìtẹríbaní oókan àyà mi;