Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 35:3-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Fa idà àti ọ̀kọ̀ yọ kí o sì dojúkọ àwọn tí ń lé mi;sọ fún ọkàn mi pé, “Èmi ni ìgbàlà Rẹ.”

4. Kí wọn kí ó dààmú, kí a sì ti àwọn tí ń lépa ọkàn mi lójú:kí a sì mú wọn padà,kí a sì dààmú àwọn tí ń gbérò ìpalára mi.

5. Jẹ́ kí wọn dà bí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́,kí ángẹ́lì Olúwakí ó máa lé wọn kiri.

6. Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó sókùnkùnkí ó sì máa yọ́,kí áńgẹ́lì Olúwakí ó máa lépa wọn!

7. Nítorí pé, ní àìnídìí ní wọ́n dẹàwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi,ní àìnídìí ni wọ́n wa kòtòfún ọkàn mi.

8. Jẹ́ kí ìparun kí ó wá síorí wọn lójijì.Àwọ̀n Rẹ̀ tí ó dẹ pamọ́,kí ó mú àwọn tìkálára wọn;kí wọn ṣubú sínú kòtòsí ìparun ara Rẹ̀.

9. Nígbà náà ni ọkàn miyóò yọ̀ nínú Olúwa,àní ayọ̀ ńlá nínú ìgbàlà Rẹ̀.

10. Gbogbo egúngún mi yóò wí pé,“ìwọ Olúwa,ta ni ó dà bí i Rẹ̀?O gba talákà làlọ́wọ́ àwọn tí ó lágbárajù wọ́n lọ,talákà àti aláìnílọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”

11. Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde;wọ́n bi mi léèrè àwọn ohuntí èmi kò mọ̀.

12. Wọ́n fi búburú san ire fún mi;láti sọ ọkàn mi di òfo.

13. Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni,nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn,mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀;mo fi ààwẹ̀ pọ́n ara mi lójú.Mo gba àdúrà pẹ̀lú ìtẹríbaní oókan àyà mi;

14. bí i ẹni wí pé ọ̀rẹ́ tàbí ẹ̀gbọ́nmi ní wọ́n;mo ń lọọ́ kiri bí ẹni tíń sọ̀fọ̀ fún ìyà Rẹ̀,tí o tẹríba nínú ìbànújẹ́.

15. Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ miwọ́n kó ara wọn jọ wọ́n sì yọ̀,wọ́n kó ara wọn jọ sí mi;àní àwọn tí èmi kò mọ̀wọ́n fà mí yawọ́n kò sì dákẹ́.

16. Àwọn àgàbàgebè ń ṣe yẹ̀yẹ́mi ṣíwájú àti sí wájú síiwọ́n pa eyín wọnkeke sí mi.

17. Yóò ti pẹ́tó,ìwọ Olúwa,tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ?Yọ mí kúrò nínú ìparun wọnàní ẹ̀mí i mi kúrò lọ́wọ́ kìnnìún.

18. Nígbà náà ni èmi yóò sọpẹ́ fún Ọnínú àjọ ńlá;èmi yóò máa yìn Ọ́ní àwùjọ ọ̀pọ̀ ènìyàn.

19. Má ṣe jẹ́ kí àwọn tí ń ṣe ọ̀tá mikí ó yọ̀ lórí ì mi,tàbí àwọn tí ó kórìírá miní àìní dí máa sẹ́jú sí mi.

Ka pipe ipin Sáàmù 35