Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 35:1-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Olúwa, gbógun ti àwọn tí ń gbógun tì mí;kí o sì kọ ojú ìjà sí àwọn tí ó ń bá mi í jà!

2. Di aṣà àti àpáta mú,kí o sì dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi!

3. Fa idà àti ọ̀kọ̀ yọ kí o sì dojúkọ àwọn tí ń lé mi;sọ fún ọkàn mi pé, “Èmi ni ìgbàlà Rẹ.”

4. Kí wọn kí ó dààmú, kí a sì ti àwọn tí ń lépa ọkàn mi lójú:kí a sì mú wọn padà,kí a sì dààmú àwọn tí ń gbérò ìpalára mi.

5. Jẹ́ kí wọn dà bí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́,kí ángẹ́lì Olúwakí ó máa lé wọn kiri.

6. Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó sókùnkùnkí ó sì máa yọ́,kí áńgẹ́lì Olúwakí ó máa lépa wọn!

7. Nítorí pé, ní àìnídìí ní wọ́n dẹàwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi,ní àìnídìí ni wọ́n wa kòtòfún ọkàn mi.

8. Jẹ́ kí ìparun kí ó wá síorí wọn lójijì.Àwọ̀n Rẹ̀ tí ó dẹ pamọ́,kí ó mú àwọn tìkálára wọn;kí wọn ṣubú sínú kòtòsí ìparun ara Rẹ̀.

9. Nígbà náà ni ọkàn miyóò yọ̀ nínú Olúwa,àní ayọ̀ ńlá nínú ìgbàlà Rẹ̀.

10. Gbogbo egúngún mi yóò wí pé,“ìwọ Olúwa,ta ni ó dà bí i Rẹ̀?O gba talákà làlọ́wọ́ àwọn tí ó lágbárajù wọ́n lọ,talákà àti aláìnílọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”

Ka pipe ipin Sáàmù 35