Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 18:41-47 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

41. Wọ́n kígbé fún ìrànlọ́wọ́, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí yóò rànwọ́n lọ́wọ́.àní sí Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá wọn lóhùn

42. Mo lù wọ́n gẹ́gẹ́ bí eruku níwájú afẹ́fẹ́;mo dà wọ́n síta gẹ́gẹ́ bí ẹrọ̀fọ̀.

43. Ìwọ ti gbà mí lọ́wọ́ ìkọlù àwọn ènìyàn;Ìwọ ti fi mí ṣe olórí àwọn orílẹ́ èdè;àwọn ènìyàn ti èmi kò mọ, yóò sì máa sìn mí.

44. Wéré ti wọ́n gbọ́ ohùn mi, wọ́n gbọ́ gbàmí;àwọn ọmọ àjèjì yóò fi ẹ̀tàn tẹríba fún mi.

45. Àyà yóò pá àlejò;wọn yóò sì fi ìbẹ̀rù jáde láti ibi kọ́lọ́fín wọn.

46. Olúwa wà láàyè! Olùbùkún ni àpáta mi!Gbígbé ga ní Ọlọ́run Olùgbàlà mi.

47. Òun ni Ọlọ́run tí ó ń gbẹ̀san mi,tí ó sì ń ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀ èdè tí ó wà ní abẹ́ mi,

Ka pipe ipin Sáàmù 18