Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 18:36-50 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. Ìwọ sọ ìrìn ẹsẹ mi di ńlá ní ìṣàlẹ̀ mi,kí kókó-ẹsẹ̀ mi má ṣe yẹ̀.

37. Èmi lépa àwọn ọ̀tá mi èmi sì bá wọnèmi kò sì padà lẹ́yìn wọn títí a fi run wọ́n.

38. Èmi ṣá wọn ní ọgbẹ́ tí wọn ko fi le è dìde;Wọ́n subú ní abẹ́ ẹsẹ̀ mi.

39. Nítorí ìwọ fi agbára dì mí ní amùrè fún ogun náà;ìwọ ti mú àwọn tí ó dìde si mí tẹríba ní abẹ́ ẹsẹ̀ mi

40. Ìwọ yí ẹ̀yìn àwọn ọ̀ta mí padà sí mièmi sì pa àwọn tí ó kóríra mí run.

41. Wọ́n kígbé fún ìrànlọ́wọ́, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí yóò rànwọ́n lọ́wọ́.àní sí Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá wọn lóhùn

42. Mo lù wọ́n gẹ́gẹ́ bí eruku níwájú afẹ́fẹ́;mo dà wọ́n síta gẹ́gẹ́ bí ẹrọ̀fọ̀.

43. Ìwọ ti gbà mí lọ́wọ́ ìkọlù àwọn ènìyàn;Ìwọ ti fi mí ṣe olórí àwọn orílẹ́ èdè;àwọn ènìyàn ti èmi kò mọ, yóò sì máa sìn mí.

44. Wéré ti wọ́n gbọ́ ohùn mi, wọ́n gbọ́ gbàmí;àwọn ọmọ àjèjì yóò fi ẹ̀tàn tẹríba fún mi.

45. Àyà yóò pá àlejò;wọn yóò sì fi ìbẹ̀rù jáde láti ibi kọ́lọ́fín wọn.

46. Olúwa wà láàyè! Olùbùkún ni àpáta mi!Gbígbé ga ní Ọlọ́run Olùgbàlà mi.

47. Òun ni Ọlọ́run tí ó ń gbẹ̀san mi,tí ó sì ń ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀ èdè tí ó wà ní abẹ́ mi,

48. tí ó pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mí.Ìwọ gbé mi ga ju àwọn tí ó dìde sí mi lọ;lọ́wọ́ àwọn ènìyàn alágbára ni ìwọ ti gbà mí.

49. Títí láéláé èmi yóò máa yìn ọ́ láàrin àwọn orílẹ̀ èdè, ìwọ Olúwa;Èmi yóò sì máa kọ orin ìyìn sí orúkọ Rẹ.

50. Ó fún Ọba Rẹ̀ ni ìṣẹ́gun ńlá;ó fi ìkáànú àìṣẹ̀tàn fún ẹni-àmì-òróró Rẹ̀,fún Dáfídì àti ìran Rẹ̀ títí láé.

Ka pipe ipin Sáàmù 18