Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 18:3-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Mo ké pe Olúwa, ẹni tí ìyìn yẹ fún,a ó sì gbàmí lọ́wọ́ àwọn ọ̀ta à mi.

4. Ìrora ikú yí mi kà,àti ìsàn omi àwọn ènìyàn búbúrú dẹ́rùbà mí.

5. Okùn isà òkú yí mi ká,ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí.

6. Nínú ìpọ́njú mo ké pe Olúwa;Mo sunkún sí Olúwa mi fún ìrànlọ́wọ́.Láti inú tẹ́ḿpìlì Rẹ̀, ó gbọ́ igbe mi;ẹkún mi wá sí iwájú Rẹ̀, sí inú etí Rẹ̀.

7. Ayé wárìrì, ó sì mì tìtì pẹ̀lú,ìpìlẹ̀, àwọn òkè gíga sì sídìí;wọ́n wárìrì nítorí tí ó ń bínú.

8. Èéfín ti ihò imú Rẹ̀ jáde wá;Iná ajónirun ti ẹnu Rẹ̀ jáde wá,ẹ̀yin iná bú jáde láti inú Rẹ̀.

Ka pipe ipin Sáàmù 18