Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 136:5-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Fún ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

6. Fún ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lórí omi;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

7. Fún ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé

8. Òòrùn láti jọba ọ̀sán;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

9. Òsùpá àti ìràwọ̀ láti jọba òru;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

10. Fún ẹni tí ó kọlu Éjíbítì lára àwọn àkọ́bí wọn;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

11. Ó sì mú Ísírẹ́lì jáde kúrò láàrin wọn;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

12. Pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

13. Fún ẹni tí ó pín òkun pupa ní ìyà;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

14. Ó sì mú Ísírẹ́lì kọjá láàrin Rẹ̀nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

15. Ṣùgbọ́n ó bi Fáráò àti ogun Rẹ̀ ṣubú nínú òkun pupa;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

16. Fún ẹni tí ó sin àwọn ènìyàn Rẹ̀ la ihà jánítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

17. Fún ẹni tí ó kọ lu àwọn ọba ńlá;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

18. Ó sì pa àwọn ọba olókìkínítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

19. Síónì, ọba àwọn ará Ámórìnítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

20. Àti Ógù, ọba Báṣánì;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

21. Ó sì fi ilẹ̀ wọn fúnni ní ìní,nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

22. Ìní fún Ísírẹ́lì, ìránṣẹ́ Rẹ̀,nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

Ka pipe ipin Sáàmù 136