Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 136:19-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Síónì, ọba àwọn ará Ámórìnítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

20. Àti Ógù, ọba Báṣánì;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

21. Ó sì fi ilẹ̀ wọn fúnni ní ìní,nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

22. Ìní fún Ísírẹ́lì, ìránṣẹ́ Rẹ̀,nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

23. Ẹni tí ó rántí wa ní ìwà ìrẹ̀lẹ̀ wa;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

24. Ó sì dá wa ní ìdè lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

25. Ẹni tí ó fi oúnjẹ fún àwọn ẹ̀dá gbogbonítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

26. Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run ọ̀run;nítorí tí àánú Rẹ̀ dúró láéláé.

Ka pipe ipin Sáàmù 136