Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 115:8-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn;gẹ́gẹ́ bẹ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ Rẹ̀ lé wọn.

9. Ìwọ Ísírẹ́lì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa:òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn

10. Ẹ yin ilé Árónì, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa:oun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn

11. Ẹ̀ yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa:oun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn.

12. Olúwa tí ń ṣe ìrántí wa; yóò bùkún ilé Ísírẹ́lì;yóò bùkún ilé Árónì.

13. Ìbùkún ni fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa,àti kékeré àti ńlá.

14. Olúwa yóò mú ọ pọ̀ síi síwájú àti síwájú,ìwọ àti àwọn ọmọ Rẹ̀.

15. Ẹ fi ìbùkún fún Olúwaẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.

16. Ọ̀run àní ọ̀run ni ti, Olúwa:ṣùgbọ́n ayé lo fi fún ọmọ ènìyàn.

17. Òkú kò le yìn Olúwa,tàbí ẹni tí o ti lọ sí ìṣàlẹ̀ ìdákẹ́jẹ́.

Ka pipe ipin Sáàmù 115