13. Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ Rẹ̀ kúròkí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀
14. Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba Rẹ̀ kíó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ OlúwaMá ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò
15. Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwakí o le ge ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
16. Nítorí kò rántí láti ṣàánú,ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíní sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú,kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
17. Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí Rẹ̀:bi inú Rẹ̀ kò ti dùn si ire, bẹ́ẹ̀ ni ki ó jìnnà sí ì.
18. Bí ó ti fi ègún wọ ará Rẹ̀ lásọ bí ẹ̀wùbẹ́ẹ̀ ni kí ó wá si inú Rẹ̀ bí omi
19. Jẹ́ kí o rí fún un bí aṣọ tí a dàbòó níara, àti fún àmùrè ti ó fi gbàjá nígbà gbogbo
20. Èyí ni èrè àwọn ọ̀ta mi làti ọwọ́ Olúwa wá;àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọ̀kàn mi.
21. Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa,ṣe rere fún mi nítorí orúkọ RẹNítorí ti àánú Rẹ dara, ìwọ gbà mí
22. Nítorí pé talákà àti aláìní ni mí,àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
23. Èmi ń kọja lọ bí òjiji tí óńfà sẹ́yìn,mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.