Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 109:13-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ Rẹ̀ kúròkí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀

14. Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba Rẹ̀ kíó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ OlúwaMá ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò

15. Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwakí o le ge ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.

16. Nítorí kò rántí láti ṣàánú,ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíní sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú,kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.

17. Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí Rẹ̀:bi inú Rẹ̀ kò ti dùn si ire, bẹ́ẹ̀ ni ki ó jìnnà sí ì.

18. Bí ó ti fi ègún wọ ará Rẹ̀ lásọ bí ẹ̀wùbẹ́ẹ̀ ni kí ó wá si inú Rẹ̀ bí omi

Ka pipe ipin Sáàmù 109