Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 7:5-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. wọn yóò pa ó mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin alágbèrè,kúrò lọ́wọ́ ìyàwó onírìnkurìn àti ọ̀rọ̀ ìtànjẹ rẹ̀.

6. Ní ojú fèrèsé ilé è mimo wo ìta láti ojú ù fèrèsé.

7. Mo rí i láàrin àwọn aláìmọ́kanmo sì kíyèsí láàrin àwọn ọ̀dọ́kùnrin,ọ̀dọ́ kan tí ó ṣe aláìgbọ́n.

8. Ó ń lọ ní pópónà ní tòsí i ilé alágbérè obìnrin náà,ó ń rìn lọ sí ọ̀nà ilé e rẹ̀

9. ní ìrọ̀lẹ́ bí oòrùn ṣe ń wọ̀,bí òkùnkùn ṣẹ ń bo ni lára.

10. Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan jáde wá láti pàdé rẹ̀,ó múra bí aṣẹ́wó pẹ̀lú ètè búburú.

11. (Ó jẹ́ aláriwo àti alágídí,ìdí rẹ̀ kì í jókòó nílé;

12. bí ó ti ń já níhìn ín ní ó ń já lọ́hùn úngbogbo orígun ni ó ti ń ba ní ibùba.)

13. Ó dìí mú, ó sì fẹnu kò ó ní ẹnupẹ̀lú ojú dídín ó wí pé:

14. “Mo ní ọrẹ àlàáfíà ní ilé;lónìí ni mo san ẹ̀jẹ́ mi.

15. Nítorí náà ni mo ṣe jáde wá pádé è rẹ;mo wá ọ káàkiri mo sì ti rí ọ!

16. Mo ti tẹ́ ibùṣùn mipẹ̀lú aṣọ aláràbarà láti ilẹ̀ Éjíbítì.

17. Mo ti fi nǹkan Olóòórùn dídùn sí ibùṣùn mibí i míra, álóè àti kínámónì.

18. Wá, jẹ́ kí a lo ìfẹ́ papọ̀ ní kíkún títí di àárọ̀;jẹ́ kí a gbádùn ara wa pẹ̀lú ìfẹ́!

19. Ọkọ ọ̀ mi ò sí nílé;ó ti lọ sí ìrìnàjò jínjìn.

Ka pipe ipin Òwe 7