Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 7:10-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan jáde wá láti pàdé rẹ̀,ó múra bí aṣẹ́wó pẹ̀lú ètè búburú.

11. (Ó jẹ́ aláriwo àti alágídí,ìdí rẹ̀ kì í jókòó nílé;

12. bí ó ti ń já níhìn ín ní ó ń já lọ́hùn úngbogbo orígun ni ó ti ń ba ní ibùba.)

13. Ó dìí mú, ó sì fẹnu kò ó ní ẹnupẹ̀lú ojú dídín ó wí pé:

14. “Mo ní ọrẹ àlàáfíà ní ilé;lónìí ni mo san ẹ̀jẹ́ mi.

15. Nítorí náà ni mo ṣe jáde wá pádé è rẹ;mo wá ọ káàkiri mo sì ti rí ọ!

16. Mo ti tẹ́ ibùṣùn mipẹ̀lú aṣọ aláràbarà láti ilẹ̀ Éjíbítì.

17. Mo ti fi nǹkan Olóòórùn dídùn sí ibùṣùn mibí i míra, álóè àti kínámónì.

18. Wá, jẹ́ kí a lo ìfẹ́ papọ̀ ní kíkún títí di àárọ̀;jẹ́ kí a gbádùn ara wa pẹ̀lú ìfẹ́!

19. Ọkọ ọ̀ mi ò sí nílé;ó ti lọ sí ìrìnàjò jínjìn.

Ka pipe ipin Òwe 7