Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 7:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọmọ mi, pa ọ̀rọ̀ mi mọ́,sì fi àwọn òfin mi pamọ́ sínú ọkàn rẹ.

2. Pa òfin mi mọ́, ìwọ yóò sì yètọ́jú ẹ̀kọ́ mi bí ẹyinlójú rẹ

3. Kọ wọ́n sí ọwọ́ òsì rẹ, má ṣe fi jẹunkọ wọ́n sí inú ọkàn rẹ.

4. Wí fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arábìnrin mi,”sì pe òye ní ìbátan rẹ;

5. wọn yóò pa ó mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin alágbèrè,kúrò lọ́wọ́ ìyàwó onírìnkurìn àti ọ̀rọ̀ ìtànjẹ rẹ̀.

6. Ní ojú fèrèsé ilé è mimo wo ìta láti ojú ù fèrèsé.

7. Mo rí i láàrin àwọn aláìmọ́kanmo sì kíyèsí láàrin àwọn ọ̀dọ́kùnrin,ọ̀dọ́ kan tí ó ṣe aláìgbọ́n.

8. Ó ń lọ ní pópónà ní tòsí i ilé alágbérè obìnrin náà,ó ń rìn lọ sí ọ̀nà ilé e rẹ̀

Ka pipe ipin Òwe 7