Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 29:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ẹni tí ó sì ń ṣorí kunkun lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìbáwíyóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.

2. Nígbà tí olódodo bá ń gbilẹ̀, àwọn ènìyàn a yọ̀nígbà tí ènìyàn búburú ń ṣàkóso, àwọn ènìyàn ń kórìíra.

3. Ènìyàn tí ó fẹ́ràn ọgbọ́n mú kí baba rẹ̀ láyọ̀ṣùgbọ́n ẹni ti ń bá aṣẹ́wó kẹ́gbẹ́ ba ọrọ̀ ọ rẹ̀ jẹ́

4. Nípa ìdájọ́ òdodo ni ọba fi í mú ìlú tòrò nini,ṣùgbọ́n èyí tí ń ṣojúkòkòrò àbẹ̀tẹ́lẹ̀ fà á lulẹ̀.

5. Ẹnikẹ́ni tí ó bá tan aládúgbò rẹ̀ó ń dẹ àwọ̀n de ẹsẹ̀ ẹ rẹ̀.

6. Ẹ̀ṣẹ̀ ènìyàn ibi ni ó jẹ́ ìdẹkùn rẹ̀ṣùgbọ́n olódodo le è kọrin kí ó sì máa yọ̀.

7. Olódodo ń ṣaápọn nípa ìdájọ́ òtítọ́ fún àwọn tálákà,ṣùgbọ́n kò sí ohun tí ó kan ènìyàn búburú nínú irú rẹ̀.

Ka pipe ipin Òwe 29