Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 28:12-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Nígbà tí olódodo ń lékè ariwo ayọ̀ ta;ṣùgbọ́n nígbà tí ènìyàn búburú gorí òye, àwọn ènìyàn a na pápá bora.

13. Ẹni tí ó bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kì í ṣe rere,ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jẹ́wọ́ tí ó sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀ máa ń rí àánú gbà.

14. Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí ó bẹ̀rù Olúwa nígbà gbogboṣùgbọ́n ẹni tí ó ṣé ọkàn rẹ̀ le bọ́ sínú wàhálà.

15. Bí kìnnìún tí ń ké tàbí Béárì tí ń halẹ̀ni ènìyàn búburú tí ń jọba lórí àwọn aláìlágbára.

16. Ọba tí ó jẹ gàba lórí ìlú láì gbàmọ̀ràn kò gbọ́nṣùgbọ́n ẹni tí ó kórìíra èrè ìjẹkújẹ yóò gbádùn ọjọ́ gígùn.

17. Ẹni tí ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ìpànìyànyóò máa joró rẹ̀ títí ikúmá ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ràn án lọ́wọ́.

18. Ẹni tí ìrìn rẹ̀ kò ní àbùkù wà láìléwuṣùgbọ́n ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ ayípadà yóò ṣubú lójijì.

Ka pipe ipin Òwe 28