Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 25:7-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ó sàn kí ó wí fún ọ pé, “Gòkè wá síhìn ín”ju wí pé kí ó dójú tì ọ́ níwájú ènìyàn pàtàkì.

8. Ohun tí o ti fi ojú ara rẹ rímá ṣe kánjú gbé e lọ sílé ẹjọ́ nítorí kí ni ìwọ yóò ṣe ní ìgbẹ̀yìnbí aládùúgbò rẹ bá dójú tì ọ́?

9. Bí o bá ń ṣe àwíjàre rẹ níwájú aládùúgbò rẹ,má ṣe tú àsírí tí ẹlòmíràn ní lọ́dọ̀ rẹ,

10. àìṣe bẹ́ẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ le dójú tì ọ́orúkọ burúkú tí ìwọ bá sì gba kì yóò tán láéláé.

11. Ọ̀rọ̀ tí a sọ ní àkókò tí ó yẹó dàbí èṣo wúrà nínú àpẹẹrẹ fàdákà.

12. Bí i yẹtí wúrà tàbí ohun ọ̀ṣọ́ ti wúrà dáradárani ìbáwí ọlọ́gbọ́n fún etí tí ó bá fetísílẹ̀.

13. Bí títutù òjò yìnyín ní àsíkò ìkórèni ìránṣẹ́ tí ó jẹ́ olóòtọ́ sí àwọn tí ó rán anó ń tu ọ̀gá rẹ̀ nínú.

14. Bí ojú ṣíṣú àti afẹ́fẹ́ láì sí òjòni ènìyàn tí ń yangàn nípa ẹ̀bùn tí kò fún ni.

15. Nípa ṣùúrù a lè yí ọba lọ́kàn padàahọ́n tí ń sọ̀rọ̀ rírọ̀ sí egungun.

16. Bí ìwọ bá rí oyin, jẹ ẹ́ ní ìwọ̀nbabí o bá jẹ ẹ́ jù, ìwọ yóò sì bì í.

17. Má ṣe máa lọ sí ilé aládùúgbò rẹ nígbà gbogbotàbí kí ó máa lọ ṣíbẹ̀ lálọ jù, yóò sì kórìíra rẹ.

18. Bí àdá, idà tàbí ọ̀kọ̀ tí ó múni ènìyàn tí ó jẹ́rìí èké lòdì sí aládùúgbò rẹ̀.

19. Bí eyín tí ó bàjẹ́ tàbí ẹṣẹ̀ tí ó rọni ìgbẹ́kẹ̀lé lórí aláìṣòótọ́ ní àsìkò ìdàámú.

Ka pipe ipin Òwe 25