Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 24:3-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́nípa òye sì ni ó ti fìdí múlẹ̀;

4. Nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kúnpẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.

5. Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀,ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára síi

6. Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà:nínú ìsẹ́gún ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.

7. Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrèàti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.

8. Ẹni tí ń pète ibini a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.

9. Ète òmùgọ̀ ènìyàn jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀,àwọn ènìyàn sì kórìíra ẹlẹ́gàn.

10. Bí ìwọ bá dákú lásìkò ìdààmúbáwo ni agbára rẹ ha ti kéré tó!

11. Gba àwọn tí a ń wọ́ lọ síbi ikú là;fa àwọn tó ń ta gbọ̀n-ọ́n gbọ̀n-ọ́n lọ síbi ìparun padà.

12. Bí ìwọ bá wí pé, “Ṣùgbọ́n a kò mọ nǹkankan nípa èyí,”ǹjẹ́ ẹni tí ń díwọ̀n ọkàn kò kíyèsíi? Ǹjẹ́ ẹni tí ń ṣọ́ ẹ̀mí rẹ kò mọ̀ ọ́?Ǹjẹ́ kò ní san án fún ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó ti ṣe?

Ka pipe ipin Òwe 24