Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 24:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Má ṣe ṣe ìlara àwọn ènìyàn búburúmá ṣe jẹ́ kí àwùjọ wọn wù ọ́;

2. Nítorí ọkàn wọn ń gbérò ohun búburú,ètè wọn sì ń sọ̀rọ̀ nípa dídá rúgúdù sílẹ̀.

3. Nípa ọgbọ́n ni ilé di kíkọ́nípa òye sì ni ó ti fìdí múlẹ̀;

4. Nípa ìmọ̀ ni àwọn yàrá rẹ̀ kúnpẹ̀lú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ tí ó lẹ́wà tí ó sì ṣọ̀wọ́n.

5. Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní agbára púpọ̀,ènìyàn tí ó ní ìmọ̀ sì ń ní agbára síi

6. Láti jagun, ó nílò ìtọ́sọ́nà:nínú ìsẹ́gún ni ọ̀pọ̀ onígbìmọ̀.

7. Ọgbọ́n ga ju fún aṣiwèrèàti gbọ̀ngàn ìlú níbi ibodè kò ní ohun tí yóò wí.

8. Ẹni tí ń pète ibini a ó mọ̀ bí ènìyàn ibi.

Ka pipe ipin Òwe 24