Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 21:2-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀ṣùgbọ́n, Olúwa ló ń díwọ̀n ọkàn.

3. Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nàó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí Olúwa ju ẹbọ lọ.

4. Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga,ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni!

5. Ètè àwọn olóye já sí èrèbí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá.

6. Ìṣúra tí a kójọ nípaṣẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹkùn ikú.

7. Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ,nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́.

8. Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́.

9. Ó sàn láti máa gbé ní kọ̀rọ̀ orí òrùléju láti ṣe àjọpín ilé pẹ̀lú aya oníjà.

10. Ènìyàn búburú ń fẹ́ ibialádùúgbò rẹ̀ kì í rí àánú kankan gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.

11. Nígbà tí a bá ń fìyà jẹ ẹlẹ́gàn, òpè a máa kọ́gbọ́n.

12. Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburúó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun.

13. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú,òun tìkárarẹ̀ yóò ké pẹ̀lú;ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́.

14. Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò:àti owó-àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá,dẹ́kun ìbínú líle.

15. Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́:ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.

Ka pipe ipin Òwe 21