7. Ẹnu aláìgbọ́n ni ó ba tirẹ̀ jẹ́ètè rẹ̀ sì jẹ́ ìdẹkùn fún ọkàn rẹ̀.
8. Ọ̀rọ̀ olófòófó dàbí oúnjẹ àdídùnwọ́n ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí akínyẹmí ara.
9. Ẹni tí kò ṣe déédé nínú iṣẹ́ rẹ̀arákùnrin ló jẹ́ fún apanirun.
10. Orúkọ Olúwa, ilé ìṣọ́ agbára ni;olódodo sá wọ inú rẹ̀, ó sì rí ìgbàlà.
11. Ọ̀rọ̀ olówó ni ìlú olódi wọnwọ́n rò ó bí i wí pé odi tí kò ṣe é gùn ni.
12. Sáájú ìṣubú ọkàn ènìyàn a kọ́kọ́ máa gbéragaṣùgbọ́n ìrẹ̀lẹ̀ ni ó máa ń ṣáájú ọlá.
13. Ẹni tí ó ń fèsì kí ó tó gbọ́òun náà ni ìwà òmùgọ̀ àti ìtìjú rẹ̀.
14. Ọkàn ènìyàn a máa gbé e ró nígbà àìsànṣùgbọ́n ta ni ó le forí ti ọkàn tí ó rẹ̀wẹ̀sì.
15. Ọkàn olóye ní i gba ìmọ̀;etí ọlọ́gbọ́n ní í ṣe àwárí rẹ̀.
16. Ẹ̀bùn máa ń sí ọ̀nà fún ẹni tí ń fún ni lẹ́bùna sì mú un wọlé sí ọ̀dọ̀ àwọn olókìkí.
17. Ẹni tí ó kọ́kọ́ rojọ́ máa ń dàbí i pé ó jàretítí ẹlòmíràn yóò fi bọ́ síwájú kí ó sì tú àsírí gbogbo.