Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 18:6-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ètè aláìgbọ́n dá ìjà sílẹ̀ẹnu rẹ̀ sì ń ṣokùnfà ẹgba.

7. Ẹnu aláìgbọ́n ni ó ba tirẹ̀ jẹ́ètè rẹ̀ sì jẹ́ ìdẹkùn fún ọkàn rẹ̀.

8. Ọ̀rọ̀ olófòófó dàbí oúnjẹ àdídùnwọ́n ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí akínyẹmí ara.

9. Ẹni tí kò ṣe déédé nínú iṣẹ́ rẹ̀arákùnrin ló jẹ́ fún apanirun.

10. Orúkọ Olúwa, ilé ìṣọ́ agbára ni;olódodo sá wọ inú rẹ̀, ó sì rí ìgbàlà.

11. Ọ̀rọ̀ olówó ni ìlú olódi wọnwọ́n rò ó bí i wí pé odi tí kò ṣe é gùn ni.

12. Sáájú ìṣubú ọkàn ènìyàn a kọ́kọ́ máa gbéragaṣùgbọ́n ìrẹ̀lẹ̀ ni ó máa ń ṣáájú ọlá.

13. Ẹni tí ó ń fèsì kí ó tó gbọ́òun náà ni ìwà òmùgọ̀ àti ìtìjú rẹ̀.

14. Ọkàn ènìyàn a máa gbé e ró nígbà àìsànṣùgbọ́n ta ni ó le forí ti ọkàn tí ó rẹ̀wẹ̀sì.

15. Ọkàn olóye ní i gba ìmọ̀;etí ọlọ́gbọ́n ní í ṣe àwárí rẹ̀.

16. Ẹ̀bùn máa ń sí ọ̀nà fún ẹni tí ń fún ni lẹ́bùna sì mú un wọlé sí ọ̀dọ̀ àwọn olókìkí.

Ka pipe ipin Òwe 18