9. Ẹni tí ó fojú fo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ṣẹ̀ẹ́ mú kí ìfẹ́ gbòòrò sí i.Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ń tẹnumọ́ ọ̀rọ̀ yóò pín ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ méjì níyà.
10. Ọ̀rọ̀ ìbáwí dun ènìyàn olóyeju ọgọ́rùn ún pàsán lẹ́yìn aláìgbọ́n.
11. Oríkunkun ni ènìyàn ìkà máa ń ṣe,ìjòyè aláìláàánú ni a ó rán sí i.
12. Ó sàn kí ènìyàn pàdé béárì tí a ti kó lọ́mọjù aláìgbọ́n nínú ìwà òmùgọ̀ rẹ̀.
13. Bí ènìyàn kan bá fi ibi san ire,ibi kì yóò kúrò nílé rẹ̀ láéláé.
14. Bíbẹ̀rẹ̀ ìjà dàbí ẹni tí ó dá ojú fún adágún ominítorí náà mẹ́nu kúrò nínú ọ̀rọ̀ kí ó tó di ìjà.
15. Gbígbé ẹ̀bi fún aláre àti dídá ẹni jàre lẹ́bi, Olúwa kóríra méjèèjì.
16. Kí ni ìwúlò owó lọ́wọ́ aṣiwèrèníwọ̀n bí kò ti ní èròńgbà láti rí ọgbọ́n?
17. Ọ̀rẹ́ a máa fẹ́ni nígbà gbogbo,Arákùnrin sì wà fún ìgbà ìpọ́njú.
18. Ènìyàn aláìgbọ́n ṣe ìbúraó sì ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ̀.
19. Ẹni tí ó fẹ́ràn ìjà fẹ́ràn ẹ̀ṣẹ̀;ẹni tí ó kọ́ ibodè gígàn ń wá ìparun.
20. Ènìyàn aláyìídáyidà ọkàn kì í gbèrúẹni tí ó ní ahọ́n ẹ̀tàn bọ́ sínú ìyọnu.
21. Láti bí aláìgbọ́n lọmọ a máa fa ìbànújẹ́ ọkànkò sí ayọ̀ fún baba ọmọ tí kò gbọ́n.
22. Ọkàn tí ó túká jẹ́ ogún gidiṣùgbọ́n ọkàn tí ó bàjẹ́ a máa mú kí egungun gbẹ.