Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 17:20-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Ènìyàn aláyìídáyidà ọkàn kì í gbèrúẹni tí ó ní ahọ́n ẹ̀tàn bọ́ sínú ìyọnu.

21. Láti bí aláìgbọ́n lọmọ a máa fa ìbànújẹ́ ọkànkò sí ayọ̀ fún baba ọmọ tí kò gbọ́n.

22. Ọkàn tí ó túká jẹ́ ogún gidiṣùgbọ́n ọkàn tí ó bàjẹ́ a máa mú kí egungun gbẹ.

23. Ènìyàn búburú a gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀láti yí ìdájọ́ po.

24. Olóyè ènìyàn gbójú wo ọgbọ́n níwájúṣùgbọ́n ojú aláìgbọ́n ń wò káàkiri ilẹ̀ ayé.

25. Aláìgbọ́n ọmọ mú ìbànújẹ́ bá baba rẹ̀àti ìkorò fún ẹni tí ó bí i lọ́mọ.

26. Kò dára láti fìyà jẹ ènìyàn tí kò ṣẹ̀tàbí láti na ìjòyè lórí òtítọ́ inú wọn.

27. Ènìyàn tó ní ìmọ̀ máa ń ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ń sọènìyàn olóye sì máa ń ní ṣùúrù.

28. Kódà aláìgbọ́n máa ń dàbí ọlọgbọ́n bí ó bá dákẹ́àti bí olóye bí ó bá fètèmétè.

Ka pipe ipin Òwe 17