Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 17:13-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Bí ènìyàn kan bá fi ibi san ire,ibi kì yóò kúrò nílé rẹ̀ láéláé.

14. Bíbẹ̀rẹ̀ ìjà dàbí ẹni tí ó dá ojú fún adágún ominítorí náà mẹ́nu kúrò nínú ọ̀rọ̀ kí ó tó di ìjà.

15. Gbígbé ẹ̀bi fún aláre àti dídá ẹni jàre lẹ́bi, Olúwa kóríra méjèèjì.

16. Kí ni ìwúlò owó lọ́wọ́ aṣiwèrèníwọ̀n bí kò ti ní èròńgbà láti rí ọgbọ́n?

17. Ọ̀rẹ́ a máa fẹ́ni nígbà gbogbo,Arákùnrin sì wà fún ìgbà ìpọ́njú.

18. Ènìyàn aláìgbọ́n ṣe ìbúraó sì ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ̀.

Ka pipe ipin Òwe 17