Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 16:14-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Ìrànṣẹ́ ikú ni ìbínú ọba jẹ́ṣùgbọ́n ọlọgbọ́n ènìyàn yóò tù ú nínú.

15. Nígbà tí ojú ọba bá túká, ó túmọ̀ sí ìyè;ojú rere rẹ̀ dàbí i ṣíṣú òjò ní ìgbà òjò.

16. Ó ti dára tó láti ní ọgbọ́n ju wúrà lọàti láti yan òye dípò o fàdákà!

17. Òpópó ọ̀nà àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yàgò fún ibi,ẹni tí ó ṣọ́ ọ̀nà rẹ̀, ṣọ́ ẹnu ara rẹ̀.

18. Ìgbéraga ní í ṣáájú ìparun,agídí ọkàn ní í ṣáájú ìṣubú,

19. ó sàn láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ọkàn láàrin àwọn olùpọ́njújù láti máa pín ìpín pẹ̀lú àwọn agbéraga.

20. Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé ẹ̀kọ́ yóò rí ire,ìbùkún sì ni fún ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ lé Olúwa.

21. Àwọn tí ó gbọ́n nínú ọkàn là ń pè ní olóyeọ̀rọ̀ ìtura sì ń mú ẹ̀kọ́ gbèrú.

22. Òye jẹ́ oríṣun ìyè fún àwọn tí ó ní i,ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ ń kó ìyà jẹ aláìgbọ́n.

23. Ọkàn ọlọgbọ́n ènìyàn a máa ṣọ́ ẹnu rẹ̀ètè rẹ̀ sì ń mú kí ẹ̀kọ́ gbèrú.

24. Ọ̀rọ̀ ìtura dàbí afárá oyinó dùn fún ọkàn, ó sì fi ìlera fún egungun.

25. Ọ̀nà kan tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyànṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn a ṣokùnfà ikú.

26. Ìfẹ́-àti-jẹun alágbàṣe ń ṣiṣẹ́ fún unnítorí ebi rẹ̀ mú kí ó máa ṣiṣẹ́ ni.

27. Ènìyàn búburú ń pèteọ̀rọ̀ rẹ̀ sì dàbí i iná tí ń jóni.

28. Aláyìídáyidà ènìyàn dá ìjà sílẹ̀olófòófó a sì máa pín ọ̀rẹ́ kòríkòsùn níyà.

29. Oníjàgídíjàgan ènìyàn tan aládùúgbò rẹ̀ó sì mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà tí kò dára.

30. Ẹni tí ń ṣẹ́jú ń pètekéte;ẹni tí ó ṣu ẹnu jọ ń pète aburú.

31. Ewú orí jẹ́ ògoìgbé ayé òdodo ní í múni débẹ̀.

32. Ó sàn láti jẹ́ oníṣùúrù ju ajagun ènìyàn lọ,ẹni tí ó pa ìbínú mọ́ra ju ajagun-gbàlú lọ.

Ka pipe ipin Òwe 16