Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 15:5-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Aláìgbọ́n ọmọ kọ ìbáwí baba rẹ̀ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí jẹ́ ọlọgbọ́n.

6. Ilé olódodo kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìṣúra,ṣùgbọ́n èrè àwọn ènìyàn búburú ń mú ìyọnu wá fún wọn.

7. Ètè olódodo ń tan ìmọ̀ kalẹ̀;ṣùgbọ́n kò rí bẹ́ẹ̀ fún ọkàn aláìgbọ́n.

8. Olúwa kórìíra ìrúbọ àwọn ènìyàn búburúṣùgbọ́n àdúrà olódodo tẹ́ẹ lọ́rùn.

9. Olúwa kórìíra ọ̀nà àwọn ènìyàn búburúṣùgbọ́n ó fẹ́ràn àwọn tí ń lépa òdodo.

10. Ẹni tí ó kúrò lójú ọ̀nà yóò rí ìbáwí gan an,ẹni tí ó kórìíra ìbáwí yóò kú.

11. Ikú àti ìparun sí sílẹ̀ níwájú Olúwamélòó mélòó ní nínú ọkàn àwọn ènìyàn.

12. Ẹlẹ́gàn kórìíra ìbáwí:kò ní gbàmọ̀ràn lọ́dọ̀ ọlọ́gbọ́n.

13. Inú dídùn máa ń mú kí ojú túkáṣùgbọ́n ìbànújẹ́ ọkàn máa ń pa ẹ̀mí run.

14. Ọkàn olóye ń wá ìmọ̀ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n ń fẹ́ ìwà òmùgọ̀ bí ẹní jẹun.

15. Gbogbo ọjọ́ àwọn olùpọ́njú jẹ́ ibi,ṣùgbọ́n ọkàn tí ń dunnú a máa Jàṣè ṣáá.

16. Ó sàn kí ó má pọ̀, kí ìbẹ̀rù Olúwa sì wàju ọrọ̀ púpọ̀ pẹ̀lú ìyọnu.

17. Oúnjẹ ewébẹ̀ níbi tí ìfẹ́ wàsàn ju àbọ́pa màlúù tòun ti ìríra.

18. Ènìyàn onínú ríru dá ìjà sílẹ̀ṣùgbọ́n onísùúrù paná ìjà.

19. Ẹ̀gún dí ọ̀nà ọ̀lẹṣùgbọ́n pópónà tí ń dán ni ti àwọn dídúró ṣinṣin.

Ka pipe ipin Òwe 15