Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 13:2-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ènìyàn ń gbádùn àwọn ohun rereṣùgbọ́n, aláìsòótọ́ ní ìfẹ́ ọkàn láti inú ìwà ipá.

3. Ẹnikẹ́ni tí ó ṣọ́ ẹnu rẹ̀ pa ẹnu ara rẹ̀ mọ́,ṣùgbọ́n ẹni tí ó ń sọ̀rọ̀ gbàù-gbàù yóò parun.

4. Ọkàn ọ̀lẹ ń fẹ́, ṣùgbọ́n kò rí nǹkankan,ṣùgbọ́n ọkàn àwọn ti kì í ṣọ̀lẹ rí ìtẹ́lọ́rùn.

5. Olódodo kórìíra ohun tí í ṣe irọ́Ṣùgbọ́n ènìyàn búburú hu ìwà ìríra àti ìtìjú.

6. Òdodo ń ṣamọ̀nà ènìyàn olóòótọ́ inú,ṣùgbọ́n ìwà búburú sí ẹlẹ́ṣẹ̀ nípò.

7. Ènìyàn kan díbọ́n bí ẹni tí ó ní ọrọ̀ síbẹ̀ kò ní nǹkankanẹlòmííràn díbọ́n bí i talákà, síbẹ̀ ó ní ọrọ̀ púpọ̀.

8. Ọrọ̀ ènìyàn le è ra ẹ̀mí rẹ̀ṣùgbọ́n talákà kì í gbọ́ ìdẹ́rùbà.

9. Ìmọ́lẹ̀ olódodo tàn roro,ṣùgbọ́n àtùpà ènìyàn búburú ni a pa kú.

10. Ìgbéraga máa ń dá ìjà sílẹ̀ niṣùgbọ́n ọgbọ́n wà nínú àwọn tí ń gba ìmọ̀ràn.

11. Owó tí a fi ọ̀nà èrú kó jọ yóò sí lọ,ṣùgbọ́n ẹni tí ń kó owó jọ díẹ̀ díẹ̀ yóò pọ̀ síi.

12. Ìrètí tí ń falẹ̀ máa ń mú kí ọkàn ṣàárẹ̀ṣùgbọ́n ìrètí tí a rí gbà jẹ́ igi ìyè.

13. Ẹni tí ó kẹ́gàn ẹ̀kọ́ yóò jìyà rẹ̀ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa àṣẹ mọ́ gba èrè rẹ̀.

14. Ìkọ́ni ọlọ́gbọ́n jẹ́ orísun ìyè,tí ń yí ènìyàn padà kúrò nínú ìdẹkùn ikú.

15. Òye pípé ń mú ni rí ojú rereṢùgbọ́n ọ̀nà aláìsòótọ́ kì í tọ́jọ́.

16. Gbogbo olóye ènìyàn máa ń hùwà pẹ̀lú ìmọ̀Ṣùgbọ́n aláìgbọ́n a fi ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ hàn.

17. Ìránṣẹ́ búburú bọ́ sínú ìdàámúṣùgbọ́n aṣojú olóòtọ́ mú ìwòsàn wá.

18. Ẹni tí ó kọ ìbáwí yóò di talákà yóò sì rí ìtìjú,ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí ni yóò rí ọlá.

Ka pipe ipin Òwe 13