Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Sólómónì 8:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ìwọ ìbá rí bí arákùnrin misí mi èyí tí ó mú ọmú ìyá mi dàgbà!Èmi ìbá rí ọ ní òde,èmi ìbá fi ẹnu kò ọ́ ní ẹnu,wọn kì bá fi mi ṣe ẹlẹ́yà.

2. Èmi ìbá fi ọ̀nà hàn ọ́èmi ìbá mú ọ wá sínú ilé ìyámi, ìwọ ìbá kọ́ mièmi ìbá fi ọtí wáìnì olóòrùn dídùn fún ọ muàti oje èso pómégíránéètì mi.

3. Ọwọ́ òsì rẹ ìbá wà ní abẹ́ orí mi,ọwọ́ ọ̀tún rẹ ìbá sì gbá mí mọ́ra.

4. Ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mù, èmi pè yín ní ìjà,Ẹ má ṣe rú olùfẹ́ mi sókè,Ẹ má ṣe jí i títí tí yóò fi wù ú.

5. Ta ni ẹni tí ń gòkè bọ̀ wá láti ihà,tí ó fi ara ti olùfẹ́ rẹ̀ní abẹ́ igi ápù ni mo ti jí ọ dìde;níbẹ̀ ni ẹni tí ń rọbí bí ọ sí.

6. Gbé mi sí àyà rẹ bí èdìdìbí èdìdì lé apá rẹ;nítorí ìfẹ́ lágbára bí ikú,ìjowú sì le bí isà òkújíjò rẹ̀ rí bí ìjò iná,gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ iná Olúwa.

7. Omi púpọ̀ kò le paná ìfẹ́;Bẹ́ẹ̀ ni gbígbá omi kò le gbá a lọ.Bí ènìyàn bá fún ìfẹ́,ní gbogbo ọrọ̀ ilé rẹ̀,a ó kẹ́gàn rẹ̀ pátapáta.

Ka pipe ipin Orin Sólómónì 8