Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 5:16-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Èéṣe tí ìwọ fi jókòó láàárin agbo àgùntànláti máa gbọ́ fèrè olùsọ́-àgùntàn?Ní ipadó Rúbẹ́nìni ìgbèrò púpọ̀ wà.

17. Gílíádì jókòó ní òkè odò Jọ́dánì.Èéṣe tí Dánì fi jókòó nínú ọkọ̀ ojú omi?Ásérì jòkòó ní etí bèbè òkun,ó sì n gbé èbúté rẹ̀.

18. Àwọn ènìyàn Ṣébúlúnì fi ẹ̀mí wọn wéwu ikú;bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ènìyàn Náfítalì ní ibi gíga pápá.

19. “Àwọn ọba wá, wọ́n sì jà;àwọn ọba Kénánì jàní Tánákì ní etí odo Mégídò,ṣùgbọ́n wọn kò sì gba èrè owó.

20. Àwọn ìràwọ̀ já láti ojú ọ̀run wáláti ibùjókòó wọn ni wọ́n ti bá Ṣísérà jà.

21. Odò Kísónì agbá wọn lọ,odò àtijọ́ náà, odò Kíṣónì.Má a yan lọ ìwọ ọkàn mi, jẹ́ alágbára pẹ̀lú!

Ka pipe ipin Onídájọ́ 5