Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 3:11-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún títí tí Ótíníẹ́lì fi kú.

12. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì tún padà sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn, wọ́n sì ṣe èyí tí ó burú ní iwájú Olúwa, fún ìdí iṣẹ́ búburú yìí. Olúwa fún Égílónì, ọba àwọn Móábù ní agbára ní orí Ísírẹ́lì.

13. Pẹ̀lú ìfi ọwọ́ ṣowọ́pọ̀ ogun àwọn Ámórì àti àwọn ọmọ ogun Ámálékì ní Égílónì gbógun ti àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, wọ́n sì gba ìlú Ọ̀pẹ (Jẹ́ríkò).

14. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì sin Égílónì ọba Móábù fún ọdún méjìdínlógún

15. Ṣùgbọ́n nígbà tí Ísírẹ́lì tún ké pe Olúwa, Olúwa rán olùgbàlà sí wọn, Éhúdù ẹni tí ń lo ọwọ́ òsì, ọmọ Gérà ti ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì. Éhúdù ni àwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa ń fi owó orí wọn rán sí Égílónì olú ìlú Móábù ní ọdọọdún fún ọdún mẹ́rìndínlógún.

16. Ṣùgbọ́n kí ó tó lọ ní ọdún yìí Éhúdù ti ṣe idà mímú olójú méjì kan tí gígùn rẹ̀ fẹ́ ẹ̀ tó ẹṣẹ̀ kan ààbọ̀, ó sì fi pamọ́ sínú àwọn aṣọ rẹ̀ tí ó so mọ́ itan rẹ̀ ọ̀tún.

17. Éhúdù gbé owó orí náà lọ bí ó ti máa ń ṣe tẹ́lẹ̀ ó sì fi fún Égílónì ẹni tí ó sanra púpọ̀.

18. Lẹ́yìn tí ó ti fi ẹ̀bùn náà fún ọba tan, ó rán àwọn tí ó kó ẹrú náà wá lọ sí ọ̀nà wọn.

Ka pipe ipin Onídájọ́ 3