Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 20:36-41 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. Àwọn ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì sì rí pé wọ́n ti ṣẹ́gun àwọn.Àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì fà sẹ́yìn níwájú àwọn ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì nítorí pé wọ́n fọkàn tán àwọn tí ó wà ní ibùba ní ẹ̀bá Gíbíà.

37. Àwọn ọkùnrin tí wọ́n lúgọ yára jáde wọ́n sì tètè wọ Gíbíà, wọ́n fọ́nká wọ́n sì fi idà pa gbogbo àwọn tí ó wà nínú ìlú náà.

38. Àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì àti àwọn tí ó lúgọ sínú igbó ti fún ara wọn ní àmì pé, kí àwọn tí ó lúgọ fi ẹ̀ẹ́fín ṣe ìkúukùú ńlá láti inú ìlú náà,

39. nígbà náà ni àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì yípadà, wọ́n sá gun.Àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ṣẹ́gun àti ní pípa àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì tí ó to ọgbọ̀n (30), wọ́n sì wí pé, “Àwa ń ṣẹ́gun wọn bí ìgbà ìjà àkọ́kọ́.”

40. Ṣùgbọ́n nígbà tí ìkúukùú ẹ̀ẹ́fín bẹ̀rẹ̀ sí ní rú sókè láti inú ìlú náà wá, àwọn ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì yípadà wọ́n sì rí ẹ̀ẹ́fín gbogbo ìlú náà ń gòkè sí ojú ọ̀run.

41. Àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì sì yípadà sí wọn, ẹ̀rù gidigidi sì ba àwọn ará Bẹ́ńjámínì nítorí pé wọ́n mọ̀ pé àwọn wà nínú ewu.

Ka pipe ipin Onídájọ́ 20