Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 2:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọjọ́ kan ańgẹ́lì Olúwa dìde kúrò láti Gígálì lọ sí Bókímù ó sì wí pé, “Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Éjíbítì wá, èmi sì ṣíwájú yín wá sí ilẹ̀ tí mo ti ṣèlérí láti fi fún àwọn baba ńlá yín. Èmi sì wí pé, ‘Èmi kì yóò yẹ májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín.

2. Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ bá àwọn ènìyàn ilẹ̀ yí dá májẹ̀mú àlàáfíà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò wó pẹpẹ ibi ìsin òrìṣà wọn lulẹ̀.’ Ṣíbẹ̀ ẹ̀yin ṣe àìgbọ́ràn sími. Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí?

3. Ní báyìí, èmi wí fún un yín pé, èmi kì yóò lé àwọn ènìyàn jáde kúrò níwájú yín; ṣùgbọ́n wọn yóò jẹ́ ẹ̀gún ní ìhà yín, àwọn òrìṣà wọn yóò sì jẹ́ ìdánwò fún un yín.”

4. Bí ańgẹ́lì Olúwa sì ti sọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ará Ísírẹ́lì tan, àwọn ènìyàn náà sì gbé ohùn wọn sókè wọ́n sì sunkún kíkorò,

Ka pipe ipin Onídájọ́ 2