Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 18:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kò ní ọba.Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àwọn ẹ̀yà Dánì ń wá ilẹ̀ ti wọn, níbi tí wọn yóò máa gbé, nítorí pé títí di àkókò náà wọn kò ì tí ì pín ogún ilẹ̀ fún wọn ní ìní láàárin àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.

2. Nítorí náà àwọn ẹ̀yà Dánì rán àwọn jagunjagun márùn ún lọ láti Ṣórà àti Ésítaólì láti yọ́ ilẹ̀ náà wò àti láti rìn ín wò. Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe ojú fún gbogbo àwọn ẹ̀yà wọn. Wọ́n wí fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ rin ilẹ̀ náà ká, kí ẹ sì wò ó fínnífínní.”Àwọn ọkùnrin náà wọ àwọn ìlú tí ó wà ní agbégbé òkè Éfúráímù, wọ́n sì dé ilé Míkà, níbi tí wọ́n sùn ní òru náà.

3. Nígbà tí wọ́n súnmọ́ tòsí ilé e Míkà, wọ́n dá ohùn ọ̀dọ́mọkùnrin Léfì náà mọ̀, torí náà wọ́n yípadà, wọ́n sì wọ inú ilé náà lọ wọ́n sì bi í pé, “Tá ni ó mú ọ wa sí ibi? Kí ni ìwọ ń ṣe níhìnìnyìí? Èéṣe tí o fi wà ní ibí?”

4. Ó sọ ohun tí Míkà ti ṣe fún un, ó fi kún un fún wọn pé, “Ó gbà mí sí iṣẹ́, èmi sì ni àlùfáà rẹ̀.”

5. Wọ́n wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ béèrè ní ọwọ́ Ọlọ́run, kí àwa lè mọ̀ bí ìrìnàjò wa yóò yọrí sí rere.”

Ka pipe ipin Onídájọ́ 18