Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 14:17-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Fún gbogbo ọjọ́ méje tí wọ́n fi ṣe àsè náà ni ó fi sunkún, nítorí náà ní ọjọ́ keje ó sọ ìtúmọ̀ rẹ̀ fún un nítorí pé ó yọ ọ́ lẹ́nu ní ojoojúmọ́. Òun náà sì sọ ìtúmọ̀ àlọ́ náà fún àwọn ènìyàn rẹ̀

18. Kí ó tó di àṣálẹ́ ọjọ́ keje àwọn ọkùnrin ìlú náà sọ fún un pé,“Kí ni ó dùn ju oyin lọ?Kí ni ó sì lágbára ju kìnìún lọ?”Sámúsónì dá wọn lóhùn pé,“Bí kì í bá ṣe pé ẹ fi ọ̀dọ́ màlúù mi kọ ilẹ̀,ẹ̀yin kò bá tí mọ ìtumọ̀ sí àlọ́ mi.”

19. Lẹ́yìn èyí, ẹ̀mí Olúwa bà lé e pẹ̀lú agbára. Ó lọ sí Ásíkélónì, ó pa ọgbọ̀n (30) nínú àwọn ọkùnrin wọn, ó gba àwọn ohun ìní wọn, ó sì fi àwọn aṣọ wọn fún àwọn tí ó sọ ìtumọ̀ àlọ́ náà. Ó sì padà sí ilé baba rẹ̀ pẹ̀lú ìbínú ríru.

20. Wọ́n sì fi ìyàwó Sámúsónì fún ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, tí ó jẹ́ ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ rẹ̀ nígbà ìgbéyàwó rẹ̀.

Ka pipe ipin Onídájọ́ 14