Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 14:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà kan Sámúsónì gòkè lọ sí Tímínà níbẹ̀ ni ó ti rí ọmọbìnrin Fílístínì kan.

2. Nígbà tí ó darí (padà sílé) dé, ó sọ fún àwọn òbí rẹ̀ (baba àti ìyá rẹ̀) pé, “Mo rí obìnrin Fílístínì kan ní Tímínà: báyìí ẹ fẹ́ ẹ fún mi bí aya mi”

3. Baba àti ìyá rẹ̀ dáhùn pé, ṣé kò sí obìnrin tí ó dára tí ó sì tẹ́ ọ lọ́rùn ní àárin àwọn ìbátan rẹ, tàbí láàárin gbogbo àwọn ènìyàn wa? Ṣé ó di túlàsì fún ọ láti lọ sí àárin àwọn Fílístínì aláìkọlà kí o tó fẹ́ ìyàwó?Ṣùgbọ́n Sámúsónì wí fún baba rẹ̀ pé, “Fẹ́ ẹ fún mi torí pé inú mi yọ́ síi púpọ̀ púpọ̀.”

Ka pipe ipin Onídájọ́ 14