Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 11:37-40 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

37. Ṣùgbọ́n yọ̀ǹda ìbéèrè kan yìí fún mi, gbà mí láàyè oṣù méjì láti rìn ká orí àwọn òkè, kí n ṣunkún pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ mi torí mo jẹ́ wúndíá tí n kò sì ní lè ṣe ìgbéyàwó.”

38. Jẹ́fítà dá lóhùn pé, “Ìwọ lè lọ.” Ó sì gbà á láàyè láti lọ fún oṣù méjì. Òun àti àwọn ọmọbìnrin yóòkù lọ sí orí àwọn òkè, wọ́n ṣunkún nítorí pé kì yóò lè ṣe ìgbéyàwó.

39. Lẹ́yìn oṣù méjì náà, ó padà tọ baba rẹ̀ wá òun sì ṣe sí i bí ẹ̀jẹ́ tí ó ti jẹ́. Ọmọ náà sì jẹ́ wúndíá tí kò mọ ọkùnrin rí.Èyí sì bẹ̀rẹ̀ àṣà kan ní Ísírẹ́lì

40. wí pé ní ọjọ́ mẹ́rin láàrin ọdún àwọn obìnrin Ísírẹ́lì a máa lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti ṣe ìrántí ọmọbìnrin Jẹ́fítà ti Gílíádì.

Ka pipe ipin Onídájọ́ 11