Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 7:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà tí Móṣè ti pári gbígbé àgọ́ dúró, ó ta òróró sí i, ó sì yà á sí mímọ́ pẹ̀lú gbogbo àwọn ohun èlò rẹ̀, Ó tún ta òróró sí pẹpẹ, ó sì yà á sí mímọ́ pẹ̀lú gbogbo ohun èlò rẹ̀.

2. Nígbà náà ni àwọn olórí Ísírẹ́lì, àwọn ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, àwọn alábojútó àwọn tí a kà náà mú ọrẹ wá.

3. Wọ́n mú ọrẹ wọn wá ṣíwájú Olúwa: kẹ̀kẹ́ ẹrù mẹ́fà ti abo, àti akọ màlúù kan láti ọ̀dọ̀ olórí kọ̀ọ̀kan àti kẹ̀kẹ́ ẹrù kan láti ọ̀dọ̀ olórí méjì. Wọ́n sì kó wọn wá sí iwájú àgọ́.

4. Olúwa sọ fún Mósè pé:

5. “Gba gbogbo nǹkan wọ̀nyí lọ́wọ́ wọn, kí wọ́n ba à lè wúlò fún iṣẹ́ inú Àgọ́ Ìpàdé. Kó wọn fún àwọn ọmọ Léfì gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ẹnì kọ̀ọ̀kan bá ṣe nílò rẹ̀.”

6. Mósè sì kó àwọn kẹ̀kẹ́ ẹrù àti akọ màlúù náà fún àwọn ọmọ Léfì.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 7