Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 4:27-37 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. Gbogbo iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Gáṣónì yálà ni iṣẹ́ ṣíṣe tàbí ní ẹrù rírù ni, Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni yóò máa darí wọn; ìwọ ni kí o sì yàn ẹrù tí oníkálùkù yóò rù fún un.

28. Èyí ni iṣẹ́ ìdílé àwọn Gáṣónì ni Àgọ́ Ìpàdé Ítamárì, ọmọ Árónì tí í ṣe àlùfáà ni yóò sì jẹ alábojútó iṣẹ́ wọn.

29. “Ka iye àwọn ọmọ Mérárì nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.

30. Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní Àgọ́ Ìpàdé.

31. Iṣẹ́ tí wọn yóò sì máa ṣe nínú Àgọ́ Ìpàdé nìyìí: gbígbẹ́ àwọn férémù àgọ́, pákó ìdábú rẹ̀, òpó àti ihò òpó rẹ̀,

32. Pẹ̀lú gbogbo òpó tó yí àgbàlá ká àti ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn kí o sì yan ohun tí oníkálùkù yóò rù fún un;

33. Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Mérárì, bí wọn yóò ti máa ṣiṣẹ́ ní Àgọ́ Ìpàdé lábẹ́ àkóso Ítamárì ọmọ Árónì tí í ṣe àlùfáà.”

34. Mósè àti Árónì pẹ̀lú àwọn olórí ìjọ ènìyàn ka àwọn ọmọ Kóhátì nípa ìdílé àti ilé baba wọn.

35. Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní Àgọ́ Ìpàdé.

36. Iye wọn nípa ìdílé jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlá ó dín àádọ́ta (2,750).

37. Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Kóhátì tó ń ṣiṣẹ́ ní Àgọ́ Ìpàdé; tí Mósè àti Árónì kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mósè.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 4