17. “Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Élíásárì àlùfáà àti Jóṣúà ọmọ Núnì.
18. Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
19. Èyí ni orúkọ wọn:Kálẹ́bù ọmọ Jéfúnè,láti ẹ̀yà Júdà;
20. Ṣémúélì ọmọ Ámíhúdì,láti ẹ̀yà Ṣíméónì;
21. Élídádì ọmọ Kísílónì,láti ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì;
22. Búkì ọmọ Jógílì,láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dánì;
23. Háníélì ọmọ Éfódù,láti ẹ̀yà Mánásè, olórí àwọn ọmọ Jóṣẹ́fù,
24. Kémúélì ọmọ Ṣífílánì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Éfúráímù, ọmọ Jóṣẹ́fù;
25. Élísáfánì ọmọ Pánákì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Ṣébúlunì;
26. Pátíélì ọmọ Ásánì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Ísákárì;
27. Áhíhúdù ọmọ Ṣélómì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Áṣérì;
28. Pédàhẹ́lì ọmọ Ámíhúdì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Náfitalì.”
29. Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní ilẹ̀ Kénánì.