Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 34:17-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. “Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Élíásárì àlùfáà àti Jóṣúà ọmọ Núnì.

18. Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.

19. Èyí ni orúkọ wọn:Kálẹ́bù ọmọ Jéfúnè,láti ẹ̀yà Júdà;

20. Ṣémúélì ọmọ Ámíhúdì,láti ẹ̀yà Ṣíméónì;

21. Élídádì ọmọ Kísílónì,láti ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì;

22. Búkì ọmọ Jógílì,láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dánì;

23. Háníélì ọmọ Éfódù,láti ẹ̀yà Mánásè, olórí àwọn ọmọ Jóṣẹ́fù,

24. Kémúélì ọmọ Ṣífílánì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Éfúráímù, ọmọ Jóṣẹ́fù;

25. Élísáfánì ọmọ Pánákì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Ṣébúlunì;

26. Pátíélì ọmọ Ásánì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Ísákárì;

27. Áhíhúdù ọmọ Ṣélómì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Áṣérì;

28. Pédàhẹ́lì ọmọ Ámíhúdì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Náfitalì.”

29. Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní ilẹ̀ Kénánì.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 34