Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 33:34-49 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

34. Wọ́n kúrò ní Jótíbátà wọ́n sì pàgọ́ ní Ábírónà.

35. Wọ́n kúrò ní Ábírónà wọ́n sì pàgọ́ ní Esoni-Gébérì.

36. Wọ́n kúrò ní Esoni-Gébérì wọ́n sì pàgọ́ ní Kádésì nínú ihà Ṣínì.

37. Wọ́n kúrò ní Kádésì wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hórì, lẹ́bá Édómù.

38. Nípa àsẹ Olúwa, Árónì àlùfáà gùn orí òkè Hórì, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kárun, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ti ilẹ̀ Éjíbítì jáde wá.

39. Árónì jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hórì.

40. Àwọn ará Kénánì, ọba Árádì, tí ń gbé ìhà gúṣù ní ilẹ̀ Kénánì gbọ́ pé àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń bọ̀.

41. Wọ́n kúrò ní orí òkè Hórì, wọ́n sì pàgọ́ ní Ṣálímónà.

42. Wọ́n kúrò ní Ṣálímónà wọ́n sì pàgọ́ ní Púnónì.

43. Wọ́n kúrò ní Púnónì wọ́n sì pàgọ́ ní Óbótù.

44. Wọ́n kúrò ní Óbótù wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Ábárímù, ní agbégbé Móábù.

45. Wọ́n kúrò ní Íyímù wọ́n sì pàgọ́ ní Díbónì-Gádì.

46. Wọ́n kúrò ní Dibónì-Gádì wọ́n sì pàgọ́ ní Alimoni-Díbílátamù.

47. Wọ́n kúrò ní Alimoni-Díbílátaímù wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Ábárímù lẹ́bá Nébò.

48. Wọ́n kúrò ní orí òkè Ábárímù wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Móábù lẹ́bá Jọ́dánì ní ìkọjá Jẹ́ríkò.

49. Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Móábù wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jọ́dánì láti Bẹti-Jéíóù títí dé Abeli-Sítímù

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 33