Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 31:6-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Mósè rán wọn lọ sí ogun, ẹgbẹ̀rún (1000) láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú Fínéhásì ọmọ Élíásárì, ti ó jẹ́ àlùfáà, ti òun ti ohun èlò ibi mímọ́ àti ìpè wọ̀n-ọn-nì ní ọwọ́ rẹ̀.

7. Wọ́n dojú ìjà kọ Mídíánì gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti láṣẹ fún Mósè, kí wọn sì pa gbogbo wọn.

8. Wọ́n sì pa àwọn ọba Mídíánì pẹ̀lú: àwọn ìyókù tí wọ́n pa lára wọn ni Éfì, Rékémù, Ṣúrù àti Húrì, àti Rébà: ọba Mídíánì márùn ún, wọ́n sì fi idà pa Bálámù ọmọ Béórì.

9. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì mú gbogbo obìnrin Mídíánì ní ìgbékùn àti àwọn ọmọ kékeré wọn, wọ́n sì kó gbogbo ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo agbo ẹran wọn àti gbogbo ẹrù wọn.

10. Wọ́n finá jó gbogbo ìlú wọn àti ibùdó wọn.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 31